Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 38:15-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Ṣùgbọ́n sí ọ Olúwa,ìwọ ni mo dúró dè;ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run mi,ẹni tí yóò dáhùn.

16. Nítorí tí mo gbàdúrà,“Gbóhùn mi, kí wọn má ba à yọ̀ mí;nígbà tí ẹsẹ̀ mi bá yọ̀wọn yóò máa gbé ara wọn ga sí mi”.

17. Nítorí tí mo ti ṣe tán láti ṣubú,ìrora mi sì wà pẹ̀lú mi nígbà gbogbo.

18. Mo jẹ́wọ́ ìrékọjá mi;àánú sì ṣe mí fún ẹ̀ṣẹ̀ mi.

19. Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá miláì ní ìdí pàtàkì, wọ́n lágbára púpọ̀,ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ókórìírá mi lọ́nà òdì.

20. Àwọn tí wọn ń fiibi san rere fún miàwọn ni ọ̀ta minítorí pé mò ń tọ ire lẹ́yìn.

21. Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀,ìwọ Olúwa!Ọlọ́run miMá ṣe jìnnà sí mi

22. Yára láti ràn mí lọ́wọ́, Olúwa,Olùgbàlà mi.

Ka pipe ipin Sáàmù 38