1. OlúwaMá ṣe bá mi wí nínú ìbínú Rẹ,bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe fi ìyà jẹ mínínú ìrunú Rẹ̀.
2. Nítorí tí ọfà Rẹkàn mọ́ mi ṣinṣin,ọwọ́ Rẹ sìkì mí mọ́lẹ̀.
3. Kò sí ibi yíyè ní ara à minítorí ìbínú Rẹ;kò sí àlàáfíà nínú egungun minítorí i ẹ̀ṣẹ̀ mi.
4. Nítorí àìṣedédé miti borí mi mọ́lẹ̀;wọ́n tó ìwọ̀n bi àjàgàtí ó wúwo jù fún mi:
5. Ọgbẹ́ mi ń rùnó sì díbàjẹ́nítorí òmùgọ̀ mi;
6. Èmi ń jòwèrè:orí mi tẹ̀ ba gidigidièmi ń sọ̀fọ̀ rìn kiri ní gbogbo ọjọ́.
7. Nítorí ẹ̀gbẹ́ mi kún fún ìgbóná ti ń jó nikò sì sí ibi yíyè ní ara mi,
8. Ara mi hù, a sì wó mi jégéjégé;mo ké rora nítorí ìrúkèrúdò àyà mi.
9. Olúwa,gbogbo a áyun mi ń bẹ níwájú Rẹ;ìmí ẹ̀dùn mi kò sá pamọ́ fún ọ.
10. Àyà mi ń mí hẹlẹ,agbára mi yẹ̀ mí sílẹ̀bí ó ṣe ti ìmọ́lẹ̀ ojú mi ni,ó ti lọ kúrò lára mi.
11. Àwọn ọ̀rẹ́ miàti àwọn ẹlẹgbẹ́ midúró lókèèrè rérékúrò níbi ìpọ́njú mi,àwọn alábàágbé é mi,dúró lókèèrè.
12. Àwọn tí n wá ẹ̀mí midẹ okùn sílẹ̀ fún mi;àti àwọn tí ó fẹ́ pa mí lárań sọ̀rọ̀ nípa ìparun,wọ́n sì ń gbérò ẹ̀tàn ní gbogbo ọjọ́.
13. Ṣùgbọ́n mo dàbí adití odi,èmi kò gbọ́ ọ̀rọ̀;àti bí odi, tí kò le sọ̀rọ̀.
14. Ní tòótọ́,mo rí bí ọkùnrin tí kò gbọ́ràn,àti bí ẹnu ẹni tí kò sí ìjiyàn.