Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 37:9-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Nítorí pé á ó gé àwọn ènìyànbúburú kúrò,Ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de Olúwaàwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.

10. Ṣíbẹ̀ nígbà díẹ̀ síi,,àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ́nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀wo ipò Rẹ̀,wọn kì yóò sí níbẹ̀.

11. Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútùni yóò jogún ilẹ̀ náà,wọn yóò sì máa ṣe inú dídùnnínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.

12. Ènìyàn búburú di rìkísí sí olóòtọ́,wọ́n sì pa ẹyín wọn keke sí wọn;

13. Ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rin-un síàwọn ènìyàn búburú,nítorí tí ó rí wí péọjọ́ wọn ń bọ̀.

14. Ènìyàn búburú fa idà yọ,wọ́n sì tẹ àwọn ọrun wọn,láti sọ talákà àti aláìní kalẹ̀,láti pa àwọn tí ó dúró ṣinṣin.

15. Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ,àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.

16. Ohun díẹ̀ tí olódodo nísàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú.

17. Nítorí pé a ó ṣẹ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú,ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.

18. Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn adúró ṣinṣin,àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé;

Ka pipe ipin Sáàmù 37