Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 37:7-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Ìwọ dákẹ́ jẹ́ ẹ́ níwájú Olúwa,kí o sì fi sùúrù dúró dè é;má ṣe ṣe ìkanra nítorí àwọntí ń rí rere ní ọ̀nà wọn,nítorí ọkùnrin náà ti múèrò búburú ṣẹ.

8. Fàsẹ́yìn nínú inúbíbí,kí o sì kọ ìkannú sílẹ̀.Má ṣe ṣe ìkanra,nítorí pé ó gbéni sí búburú pẹ̀lú.

9. Nítorí pé á ó gé àwọn ènìyànbúburú kúrò,Ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de Olúwaàwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.

10. Ṣíbẹ̀ nígbà díẹ̀ síi,,àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ́nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀wo ipò Rẹ̀,wọn kì yóò sí níbẹ̀.

11. Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútùni yóò jogún ilẹ̀ náà,wọn yóò sì máa ṣe inú dídùnnínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.

12. Ènìyàn búburú di rìkísí sí olóòtọ́,wọ́n sì pa ẹyín wọn keke sí wọn;

13. Ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rin-un síàwọn ènìyàn búburú,nítorí tí ó rí wí péọjọ́ wọn ń bọ̀.

14. Ènìyàn búburú fa idà yọ,wọ́n sì tẹ àwọn ọrun wọn,láti sọ talákà àti aláìní kalẹ̀,láti pa àwọn tí ó dúró ṣinṣin.

15. Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ,àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.

16. Ohun díẹ̀ tí olódodo nísàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú.

17. Nítorí pé a ó ṣẹ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú,ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.

18. Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn adúró ṣinṣin,àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé;

19. Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi,àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.

20. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé,àwọn ọ̀ta Olúwa yóò dà bíẹwà oko tútù;wọn fò lọ;bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.

21. Àwọn ènìyàn búburú yá,wọn kò sì san-án padà,ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa fi fún ni;

Ka pipe ipin Sáàmù 37