23. Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wáláti ọ̀dọ̀ Olúwa wá,o si ṣe inú dídùn sí ọ̀nà Rẹ̀;
24. Bí ó tilẹ̀ ṣubúa kì yóò ta á nù pátapáta,nítorí tí Olúwa di ọwọ́ Rẹ̀ mú.
25. Èmi ti wà ni èwe,báyìí èmí sì dàgbà;ṣíbẹ̀ èmi kò ì tíi rí kia kọ olódodo ṣílẹ̀,tàbí kí irú ọmọ Rẹ̀máa ṣagbe oúnjẹ.
26. Aláàánú ni òun nígbà gbogboa máa yá ni;a sì máa bùsí i fún ni.
27. Lọ kúrò nínú ibi,kí o sì máa ṣe rere;nígbà náà ni ìwọ gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.
28. Nítorí pé Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òtítọ́,kò sì kọ àwọn ènìyàn mímọ́ Rẹ̀ sílẹ̀.Àwọn olódodo ni a ó pamọ́títí ayérayé,ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ènìyàn búburúní a ó ké kúrò.
29. Olódodo ni yóò jogún ilẹ̀ náà,yóò sì máa gbé ibẹ̀ títí ayérayé.
30. Ẹnu olódodo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n,ahọ́n Rẹ̀ a sì máa sọ̀rọ̀ ìdájọ́.
31. Òfin Ọlọ́run Rẹ̀ ń bẹní àyà wọn;àwọn ìgbẹ́sẹ̀ Rẹ̀ kì yóò yẹ̀.
32. Ènìyàn búburú ń ṣọ́ olódodo,Ó sì ń wá ọ̀nà láti pa á.
33. Olúwa kì yóò fi lé e lọ́wọ́kì yóò sì dá a lẹ́bi,nígbà tí a bá ń ṣe ìdájọ́ Rẹ̀.