Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 37:21-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Àwọn ènìyàn búburú yá,wọn kò sì san-án padà,ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa fi fún ni;

22. Nítorí àwọn tí Olúwa bá bùkúnni yóò jogún ilẹ̀ náà,àwọn tí ó fi bú ni a ó gé kúrò.

23. Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wáláti ọ̀dọ̀ Olúwa wá,o si ṣe inú dídùn sí ọ̀nà Rẹ̀;

24. Bí ó tilẹ̀ ṣubúa kì yóò ta á nù pátapáta,nítorí tí Olúwa di ọwọ́ Rẹ̀ mú.

25. Èmi ti wà ni èwe,báyìí èmí sì dàgbà;ṣíbẹ̀ èmi kò ì tíi rí kia kọ olódodo ṣílẹ̀,tàbí kí irú ọmọ Rẹ̀máa ṣagbe oúnjẹ.

26. Aláàánú ni òun nígbà gbogboa máa yá ni;a sì máa bùsí i fún ni.

27. Lọ kúrò nínú ibi,kí o sì máa ṣe rere;nígbà náà ni ìwọ gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.

28. Nítorí pé Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òtítọ́,kò sì kọ àwọn ènìyàn mímọ́ Rẹ̀ sílẹ̀.Àwọn olódodo ni a ó pamọ́títí ayérayé,ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ènìyàn búburúní a ó ké kúrò.

29. Olódodo ni yóò jogún ilẹ̀ náà,yóò sì máa gbé ibẹ̀ títí ayérayé.

30. Ẹnu olódodo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n,ahọ́n Rẹ̀ a sì máa sọ̀rọ̀ ìdájọ́.

31. Òfin Ọlọ́run Rẹ̀ ń bẹní àyà wọn;àwọn ìgbẹ́sẹ̀ Rẹ̀ kì yóò yẹ̀.

Ka pipe ipin Sáàmù 37