Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 37:2-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. nítorí pé wọn yóò gbẹbí koríko,wọn yóò sì Rẹ̀ dànùbí ewéko tútù

3. Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa,kí o sì máa ṣe rere;torí pé ìwọ yóò gbé ilẹ̀ náà,kí o sì gbádùn ààbò Rẹ̀

4. ṣe inú dídùn sí Olúwa;òun yóò sì fún ọ níìfẹ́ inú Rẹ̀.

5. Fi ọ̀nà Rẹ lé Olúwa lọ́wọ́;gbẹ́kẹ̀lée pẹ̀lú,òun yóò sì ṣe é.

6. Yóò sì mú kí òdodo Rẹ̀ jádebí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ,àti ìdájọ́ Rẹ̀ bí ọ̀sán gangan.

7. Ìwọ dákẹ́ jẹ́ ẹ́ níwájú Olúwa,kí o sì fi sùúrù dúró dè é;má ṣe ṣe ìkanra nítorí àwọntí ń rí rere ní ọ̀nà wọn,nítorí ọkùnrin náà ti múèrò búburú ṣẹ.

8. Fàsẹ́yìn nínú inúbíbí,kí o sì kọ ìkannú sílẹ̀.Má ṣe ṣe ìkanra,nítorí pé ó gbéni sí búburú pẹ̀lú.

9. Nítorí pé á ó gé àwọn ènìyànbúburú kúrò,Ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de Olúwaàwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.

10. Ṣíbẹ̀ nígbà díẹ̀ síi,,àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ́nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀wo ipò Rẹ̀,wọn kì yóò sí níbẹ̀.

11. Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútùni yóò jogún ilẹ̀ náà,wọn yóò sì máa ṣe inú dídùnnínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.

12. Ènìyàn búburú di rìkísí sí olóòtọ́,wọ́n sì pa ẹyín wọn keke sí wọn;

13. Ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rin-un síàwọn ènìyàn búburú,nítorí tí ó rí wí péọjọ́ wọn ń bọ̀.

Ka pipe ipin Sáàmù 37