Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 35:15-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Ṣùgbọ́n nínú ìkọ̀sẹ̀ miwọ́n kó ara wọn jọ wọ́n sì yọ̀,wọ́n kó ara wọn jọ sí mi;àní àwọn tí èmi kò mọ̀wọ́n fà mí yawọ́n kò sì dákẹ́.

16. Àwọn àgàbàgebè ń ṣe yẹ̀yẹ́mi ṣíwájú àti sí wájú síiwọ́n pa eyín wọnkeke sí mi.

17. Yóò ti pẹ́tó,ìwọ Olúwa,tí ìwọ yóò máa wò wọ́n lọ?Yọ mí kúrò nínú ìparun wọnàní ẹ̀mí i mi kúrò lọ́wọ́ kìnnìún.

18. Nígbà náà ni èmi yóò sọpẹ́ fún Ọnínú àjọ ńlá;èmi yóò máa yìn Ọ́ní àwùjọ ọ̀pọ̀ ènìyàn.

19. Má ṣe jẹ́ kí àwọn tí ń ṣe ọ̀tá mikí ó yọ̀ lórí ì mi,tàbí àwọn tí ó kórìírá miní àìní dí máa sẹ́jú sí mi.

20. Nítorí pé wọn kò sọ ọ̀rọ̀ àlàáfíà,ṣùgbọ́n wọ́n lóyún ọ̀rọ̀ ẹ̀tànsí àwọn ènìyàn dídákẹ́ ilẹ̀ náà.

21. Wọ́n ya ẹnu wọn gbòòrò sí mi;wọ́n sọ wí pé,“Áà! Áà!Ojú wa sì ti rí i.”

22. Ìwọ́ ti ríiÌwọ Olúwa:Má ṣe dákẹ́!Ìwọ Olúwa,Má ṣe jìnnà sí mi!

23. Jí dìde!Ru ara Rẹ̀ sókè fún ààbò mi,fún ìdí mi,Ọlọ́run mi àti Olúwa mi!

24. Dá mi láre,ìwọ Olúwa,Ọlọ́run mi,gẹ́gẹ́ bí òdodo Rẹ,kí o má sì ṣe jẹ́ kíwọn kí ó yọ̀ lórí mi!

25. Má ṣe jẹ́ kí wọn wínínú ara wọn pé,“Áà! Àti rí ohun tí ọkànwa ń fẹ́:Má ṣe jẹ kí wọn kí ó wí pé,a ti gbé e mì.”

26. Kí ojú kí ó tì wọ́n,lí wọn kí ó sì dààmú pọ̀,tí ń yọ̀ sí ìyọnu mikí a fi ìtìjú àti àbùkù wọ̀ wọ́n ní aṣọtí ń gbéraga sí mi.

Ka pipe ipin Sáàmù 35