Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 34:17-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Nígbà tí Olódodo bá ké fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa a máa gbọ́, a sì yọ wọ́n jáde láti inú gbogbo wàhálà wọn.

18. Olúwa sún mọ́ etí ọ̀dọ̀ àwọn oníròbìnújẹ́ ọkàn;ó sì gba irú àwọn tí i ṣe oníròra ọkàn là.

19. Ìpọ́njú àwọn olódodo pọ̀,ṣùgbọ́n Olúwa gbà wọ́n kúrò nínú gbogbo Rẹ̀.

20. Ó pa gbogbo egungun wọn mọ́;kò sí ọ̀kan tí ó dá nínú wọn.

21. Ibi ni ó mú ikú ìkà wá,àti àwọn tí ó kórìíra olódodo ni yóò jẹ̀bi.

22. Olúwa ra ọkàn àwọn ìránṣẹ́ Rẹ̀ padà;kò sí ọ̀kan nínú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀le tí yóò jẹ̀bi.

Ka pipe ipin Sáàmù 34