Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 34:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Èmi yóò máa fi ìbùkún fún Olúwa nígbà gbogbo;ìyìn Rẹ̀ yóò máa wà ní ẹnu mi títí láé.

2. Ọkàn mí yóò máa ṣògo nínú Olúwa;jẹ́ kí àwọn onírẹ̀lẹ̀ gbọ́ kí inú wọn kí ó sì máa dùn.

3. Gbé Olúwa ga pẹ̀lú mi;kí ẹ sì jẹ́ kí a jọ gbé orúkọ Rẹ̀ lékè.

4. Èmi wá Olúwa, ó sì dá mi lóhùn;Ó sì gbà mí kúrò nínú ìbẹ̀rù mi gbogbo.

5. Wọ́n wòó, ìmọ́lẹ̀ sì mọ́ wọn;ojú kò sì tì wọ́n

6. Ọkùnrin olùpọ́njú yí kígbe, Olúwa sì gbóhùn Rẹ̀;ó sì gbà á là kúrò nínú gbogbo ìpọ́njú Rẹ̀.

Ka pipe ipin Sáàmù 34