Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 33:2-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Ẹyin Olúwa pẹ̀lú dùùrù;ẹ máa fi ohun èlò olókùn mẹ́wàá kọrin sí i.

3. Ẹ kọ orin tuntun sí i;ẹ máa fi ọgbọọgbọ́n lu ohun èlò orin síi,pẹ̀lú ariwo ńlá.

4. Nítorí pé ọ̀rọ̀ Olúwa dúró ṣinṣin,gbogbo iṣẹ́ Rẹ̀ ni à ń ṣenínú òtítọ́.

5. Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ; ilé ayé kún fún ìdúró ṣinṣin àti àánú Olúwa.

6. Nípaṣẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ṣe dá àwọn ọ̀run,àti gbogbo àwọn ẹgbẹ́ ogun wọn nípa ìmísí ẹnu Rẹ̀.

7. Ó kó àwọn omi òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò;ó sì fi ibú sí ilé ìṣúra gbogbo.

8. Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù Olúwa:jẹ́ kí gbogbo àwọn olùgbé ayékí ó wà nínú ìbẹ̀rù Rẹ̀.

9. Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀; ó pàṣẹó sì dúró ṣinṣin.

10. Olúwa ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀ èdè wá sí asán;ó sì mú àrékérekè àwọn ènìyàn di ṣíṣákìí.

11. Ìgbìmọ̀ Olúwa dúró títí ayérayé,àní ìrò inú Rẹ̀ láti ìrandíran ni.

12. Ìbùkún ni fún orílẹ̀ èdè náà Ọlọ́run ẹni tí Olúwa jẹ́ tirẹ̀,àti àwọn ènìyàn náà tí ó ti yàn ṣe ìní Rẹ̀.

13. Olúwa wò láti ọ̀run wá;Ó sì rí gbogbo ìran ènìyàn.

14. Níbi tí ó ti jókòó lóríi ìtẹ́Ó wo gbogbo àwọn olùgbé ayé

Ka pipe ipin Sáàmù 33