Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 30:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Èmi yóò kókìkíì Rẹ, Olúwa,nítorí ìwọ ni ó gbé mi lékètí ìwọ kò sì jẹ́ kí àwọn ọ̀ta mi kí ó yọ̀ mí.

2. Olúwa Ọlọ́run mi, èmí ké pè ọ́, fún ìrànlọ́wọ́ìwọ sì ti wò mí sàn.

3. Olúwa, ìwọ ti yọ ọkàn mi jáde kúrò nínú isà òkúmú mi padà bọ̀ sípò alààyè kí èmi má baà lọ sínú ihò.

4. Kọ orin ìyìn sí Olúwa, ẹ̀yin olódodo;kí ẹ sì fi ọpẹ́ fún orúkọ Rẹ̀ mímọ́.

5. Nitorí pé ìbínú Rẹ̀ wà fún ìgbà díẹ̀,ojúrere Rẹ̀ wà títí ayeraye;Ẹkún lè pẹ́ títí di alẹ́,Ṣùgbọ́n ayọ̀ yóò wá ní òwúrọ̀.

6. Ní ìgbà ayé mi, mo wí pé,“a kì yóò sí mi nípò padà.”

7. Nípa ojúrere Rẹ̀, Olúwa,ìwọ ti gbé mi kalẹ̀ bí òkè tí ó ní agbára;ìwọ pa ojú Rẹ mọ́,àyà sì fò mí.

8. Sí ọ Olúwa, ni mo képè;àti sí Olúwa ni mo sunkún fún àánú:

Ka pipe ipin Sáàmù 30