Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 26:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa,nítorí tí mo ti ń rìn nínú ìwà òtítọ́ ọ̀ mi,mo sì ti ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú OlúwaǸjẹ́ ẹsẹ̀ mi kì yóò yẹ̀.

2. Wádìí mi wò, Ìwọ Olúwa, kí o sì dán mi wò,dán àyà àti ọkàn mi wò;

3. Nítorí ìfẹ́ ẹ̀ Rẹ tí ó dúró ṣinṣin ń bẹ níwájú mi,èmí sì ti rìn nínú òtítọ́ Rẹ.

4. Èmi kò jókòó pẹ̀lú aláìsòótọ́,bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò bá àwọn àgàbàgebè wọlé;

5. Èmi ti kórìírá àwùjọ àwọn ènìyàn búburúèmi kì yóò sì bá àwọn ènìyàn ìkà jókòó.

6. Èmí ó wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò sì yí pẹpẹ Rẹ ká Olúwa

7. Èmi yóò kọrin sókè àní orin ọpẹ́,èmi yóò sì máa sọ iṣẹ́ ìyanu Rẹ̀.

8. Áà Olúwa, èmí ń fẹ́ ilé Rẹ ní bi tí ìwọ ń gbé,àní níbi tí àgọ́ ọlá Rẹ̀ wà.

9. Má ṣe gbá mi dànù pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,tàbí ẹ̀mí mi pẹ̀lú àwọn ọkùnrin tí òǹgbẹ ẹ̀jẹ̀ ń gbẹ,

Ka pipe ipin Sáàmù 26