Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 25:16-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Yípadà sími, kí o sì ṣe oore fún mi;nítorí pé mo nìkàn wà, mo sì di olùpọ́njú.

17. Tì mí lẹ́yìn kúrò nínú ìpọ́njú àyà mi;kí o sì fà mí yọ kúrò nínú ìpọ́njú ù mi.

18. Kíyèsí ìjìyà àti wàhálà mi,kí o sì darí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi jìn.

19. Kíyẹ̀sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀tá mi,tí wọn kórìírá a mi pẹ̀lú ìwà ìkà wọn.

20. Pa ọkàn mi mọ́, kí o sì gbà mí sílẹ̀;Má ṣe jẹ́ kí a fi mí sínú ìtìjú,nítorí pé ìwọ ni ibi ìsádi mi.

21. Jẹ́ kí òtítọ́ inú àti ìdúró ṣinṣin kí ó pa mí mọ́;nítorí pé mo dúró tì ọ́.

22. Ra Ísírẹ́lì padà, Ìwọ Ọlọ́run,nínú gbogbo ìṣòro Rẹ̀!

Ka pipe ipin Sáàmù 25