Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 22:24-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Nítorí pé òun kò ṣááta, bẹ́ẹ̀ ni kò sì kórìíraìpọ́njú àwọn tí a ni lára;kò sì fi ojú Rẹ̀ pamọ́ fún miṣùgbọ́n ó gbọ́ nígbà tí mo ké pè é.

25. Lati ọ̀dọ̀ Rẹ̀ ni ẹsẹ̀ ìyìn mi nínú àwùjọ ńlá yóò ti wá;ẹ̀jẹ́ Rẹ̀ ni èmi yóò san níwájú àwọn tí o bẹ̀rù Rẹ̀

26. talákà yóò jẹ yóò sì yó;àwọn tí n wá Olúwa yóò yinjẹ́ kí ẹ̀mí Rẹ̀ wà láàyè títí ayárayé!

27. Gbogbo òpin ayé ni yóò rántíwọn yóò sì yípadà sí Olúwa,àti gbogbo ìdílé orílẹ̀ èdèni wọn yóò jọ́sìn níwájú Rẹ̀,

28. Nítorí ìjọba ni ti Olúwa.Òun ni ó ń pàṣẹ lórí àwọn orílẹ̀ èdè.

29. Bẹ́ẹ̀ náà ni gbogbo àwọn olówó ayé wọn yóò ṣe àṣè, wọn yóò sì sìn;gbogbo àwọn tí ó wọ inú ilẹ̀ lọ yóò kúnlẹ̀ ní iwájúu Rẹ̀àti ẹni ti kò le pa ọkàn ara Rẹ̀ mọ́ ni ààyè.

30. Irú ọmọ Rẹ̀ yóò sìn-in;a ó sọ fún àwọn ìran tí ń bọ nípa Olúwa,

Ka pipe ipin Sáàmù 22