Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 22:21-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ ọ kìnnìún;Kí o sì gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ìwo àgbáǹréré.

22. Èmi yóò kéde orúkọ ọ̀ Rẹ láàrin arákùnrin àti arábìnrin mi;nínú ìjọ ni èmi yóò máa yìn ọ́.

23. Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹyìn-ín!Gbogbo ẹ̀yin ìran Jákọ́bù, ẹ fi ògo fún-un!ẹ dìde fún-un tẹ̀rù tẹ̀rù, ẹ̀yin irú ọmọ Ísírẹ́lì!

24. Nítorí pé òun kò ṣááta, bẹ́ẹ̀ ni kò sì kórìíraìpọ́njú àwọn tí a ni lára;kò sì fi ojú Rẹ̀ pamọ́ fún miṣùgbọ́n ó gbọ́ nígbà tí mo ké pè é.

25. Lati ọ̀dọ̀ Rẹ̀ ni ẹsẹ̀ ìyìn mi nínú àwùjọ ńlá yóò ti wá;ẹ̀jẹ́ Rẹ̀ ni èmi yóò san níwájú àwọn tí o bẹ̀rù Rẹ̀

26. talákà yóò jẹ yóò sì yó;àwọn tí n wá Olúwa yóò yinjẹ́ kí ẹ̀mí Rẹ̀ wà láàyè títí ayárayé!

27. Gbogbo òpin ayé ni yóò rántíwọn yóò sì yípadà sí Olúwa,àti gbogbo ìdílé orílẹ̀ èdèni wọn yóò jọ́sìn níwájú Rẹ̀,

Ka pipe ipin Sáàmù 22