13. wọ́n ya ẹnu wọn, si mi bí i kìn-nìún tí ń dọdẹ kirití ń ké ramúramù.
14. A dà mí jáde gẹ́gẹ́ bí omi,gbogbo egungun mi ti yẹ̀ kúrò ní oríkèé Rẹ̀.Ọkàn mi sì dàbí i ìda;tí ó yọ́ láàrin inú un mi.
15. Agbára mí ti gbẹ bí àpáàdì,ahọ́n mí sì ti lẹ̀ mọ́ párí ẹ̀rẹ̀kẹ́ ẹ mi;ìwọ ti tẹ́ mi sínú eruku ikú.
16. Àwọn ajá yí mi ká;ọwọ́ àwọn ènìyàn ibi ti ka mi mọ́,Wọ́n gún mi lọ́wọ́, wọ́n sì gún mi lẹ́ṣẹ̀
17. Mo lè ka gbogbo àwọn egungun mi;àwọn tìkára wọn ń wò, wọ́n dójú lé mi.
18. Wọ́n pín aṣọ mi láàrin ara wọnàní lórí aṣọ mi ni wọ́n ṣẹ́ gègé.
19. Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, má ṣe jìnnà sí mi;Áà Olùrànlọ́wọ́ ọ̀ mi, yára wa fún àtìlẹ́yìn mi!
20. Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ idà,àní ẹ̀mí mi lọ́wọ́ agbára àwọn ajá.
21. Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ ọ kìnnìún;Kí o sì gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ìwo àgbáǹréré.
22. Èmi yóò kéde orúkọ ọ̀ Rẹ láàrin arákùnrin àti arábìnrin mi;nínú ìjọ ni èmi yóò máa yìn ọ́.
23. Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹyìn-ín!Gbogbo ẹ̀yin ìran Jákọ́bù, ẹ fi ògo fún-un!ẹ dìde fún-un tẹ̀rù tẹ̀rù, ẹ̀yin irú ọmọ Ísírẹ́lì!