Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 22:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọlọ́run mi, Ọlọ́run mi, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí sílẹ̀?Èéṣe tí o fi jìnnà láti gbà mí là,àní sí igbe àwọn asọ̀ mi?

2. Ọlọ́run mi, ní ọ̀sán gangan ni mo kígbe, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi ní ohùn:àti ní òru èmi kò dákẹ́.

3. Ṣùgbọ́n ṣíbẹ̀ ẹni mímọ́ ni ìwọ;ẹni tí ó tẹ ìyìn Ísírẹ́lì dó;

4. Àwọn babańlá wa ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú un Rẹ;wọ́n ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ìwọ sì gbà wọ́n.

5. Ìwọ ni wọ́n sun ẹkún sí, wọ́n sì ní ìgbàlà;ìwọ ni wọ́n gbẹ́kẹ̀lé, a kò sì dójú tì wọ́n.

6. Ṣùgbọ́n kòkòrò ní mo jẹ́ kì í sì í ṣe ènìyàn;mo di ẹlẹ́gàn àwọn ènìyàn ẹlẹ́yà àwọ́n ènìyàn

Ka pipe ipin Sáàmù 22