Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 19:9-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Ìbẹ̀rù Olúwa mọ́,ó ń faradà títí láéláé.Ìdájọ́ Olúwa dájúòdodo ni gbogbo wọn.

10. Wọn ṣọ̀wọ́n ju gólùù lọ,ju góòlù tí o dára jùlọ.wọ́n dùn ju oyin lọ,Àti ju afárá oyin lọ.

11. Nípa wọn ni a ti sí ìránṣẹ́ Rẹ̀ létí;nípa pípa wọ́n mọ́, èrè púpọ̀ ń bẹ.

12. Ta ni o lé mọ àṣìṣe Rẹ̀?Dáríjìn mí nínú àṣìṣe mi tí ó pamọ́.

13. Wẹ ìrànsẹ́ Rẹ mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àmọ̀ọ́n-mọ̀-dá;Má ṣe jẹ kí wọn kí ó jọba lórí mi.Nígbà náà ní èmí yóò dúró ṣinṣin,èmi yóò sì ṣe aláìlẹ́bi kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.

14. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹnu mi àti àṣàrò ọkàn mikí ó jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà ní ojú Rẹ,Ìwọ Olúwa, àpáta mi.àti Olùdáǹdè mi.

Ka pipe ipin Sáàmù 19