Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 18:17-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ ọ̀ta mi alágbára,láti ọwọ́ àwọn ọ̀ta, ti ó lágbára jù fún mi.

18. Wọ́n dojúkọ mí ní ọjọ́ ìpọ́njú mi;ṣùgbọ́n Olúwa ni alàtìlẹ́yìn mi.

19. Ó mú mi jáde wá sínú ibi ńlá;Ó gbà mí nítorí tí ó ní inúdídùn sí mi.

20. Olúwa ti hùwà sí mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi;gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi, ó ti fi èrè fún mi

21. Nítorí mo ti pa ọ̀nà Olúwa mọ́;èmi kò ṣe búbúrú nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi

22. Gbogbo òfin Rẹ̀ ni ó wà níwájú mi;èmi kò sì yípadà kúrò nínú ìlànà Rẹ̀.

23. Mo ti jẹ́ aláìlẹ́bi níwájú Rẹ̀;mo sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀.

Ka pipe ipin Sáàmù 18