Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 18:10-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Ó gun orí kérúbù, ó sì fò;ó ń rá bàbà lórí ìyẹ́ apá afẹ́fẹ́.

11. Ó fi òkùnkùn ṣe ibojì Rẹ̀, ó fi ṣe ìbòrí yí ara Rẹ̀ kákùrúkùrù òjò dúdú ní ojú ọ̀run.

12. Nípa ìmọ́lẹ̀ iwájú Rẹ̀, àwọ̀sánmà ṣíṣú dudu Rẹ kọja lọpẹ̀lú yìnyín àti ẹyìn iná

13. Olúwa sán àrá láti ọ̀run wá;Ohùn ẹni gíga jùlọ tí ń dún.

14. Ó ta àwọn ọfà Rẹ̀, ó sì tú àwọn ọ̀ta náà ká,ọfà mọ̀nàmọ́ná ńlá sì dà wọ́n rú.

15. A sì fi ìṣàlẹ̀ àwọn òkun hàn,a sì rí àwọn ìpìlẹ̀ ayénípa ìbáwí Rẹ̀, Olúwa,nípa fífún èémí ihò imú Rẹ.

16. Ó sọ̀kalẹ̀ láti ibi gíga ó sì dì mí mú;Ó fà mí jáde láti inú omi jínjìn.

Ka pipe ipin Sáàmù 18