Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 16:6-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Okùn ààlà ilẹ̀ ti bọ́ sí ọ̀dọ̀ mi ní ibi dídára;nítòótọ́ mo ti ní ogún rere.

7. Èmi yóò yin Olúwa, ẹni tí ó gbàmí ní ìyànjú;ní òru, ọkàn mí ń bá mi sọ̀rọ̀.

8. Mo ti gbé Ọlọ́run ṣíwájú mi ní ìgbà gbogbo.Nítorí tí ó wà ní ọwọ́ ọ̀tún mi,a kì yóò mì mí.

9. Nítorí èyí, ọkàn mi yọ̀, ahọ́n mi pẹ̀lú ń fò fáyọ̀;ara mi pẹ̀lú yóò sinmi ní ààbò,

10. nítorí ìwọ kò ní fi ọ̀kan sílẹ̀ nínú iṣà òkú,tàbí kí ìwọ jẹ́ kí ẹni mímọ́ Rẹ kí ó rí ìdíbàjẹ́.

11. Ìwọ ti fi ipa ọ̀nà ìyè hàn mí;Ìwọ yóò kún mi pẹ̀lú ayọ̀ ní ìwájú Rẹ,pẹ̀lú ìdùnnú ayérayé ní ọwọ́ ọ̀tún Rẹ.

Ka pipe ipin Sáàmù 16