Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 148:3-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ẹ fi ìyìn fún un,oòrùn àti òṣùpáẸ fi ìyìn fún un,gbogbo ẹ̀yin ìràwọ̀ ìmọ́lẹ̀.

4. Ẹ fi ìyìn fún un,ẹ̀yin ọ̀run àwọn ọ̀run gígaàti ẹ̀yin omi tí ń bẹ ní òkè ọ̀run

5. Ẹ jẹ́ kí wọn kí ó yin orúkọ Olúwanítorí ó pàṣẹ a sì dá wọn

6. Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láé àti láéláéó sì ti ṣe ìlànà kan tí kì yóò já.

7. Ẹ yin Olúwa láti ilẹ̀ ayé wáẹ̀yin ẹ̀dá inú òkun títóbiàti ẹ̀yin ibú òkun

8. Mọ̀nàmọ́ná àti òjò yìnyínìdí omi àti àwọn ìkùùku,ìjì líle tí ń mú ọ̀rọ̀ Rẹ̀ ṣẹ;

9. Òkè ńlá àti gbogbo òkè kékèké,igi eléso àti gbogbo igi kédárì,

10. Àwọn ẹranko ńlá àti ẹran ọ̀sìngbogbo ohun afàyàfà àti àwọn ẹyẹ abìyẹ́:

Ka pipe ipin Sáàmù 148