Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 147:4-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ó ka iye àwọn ìràwọ̀ó sì pe ọ̀kọ̀ọkan wọn ní orúkọ

5. Títóbi ní Olúwa wa ó sì pọ̀ ní agbáraòye Rẹ̀ kò sì ní òpin.

6. Olúwa wa pẹ̀lú àwọn onírẹ̀lẹ̀bẹ́ẹ̀ ni ó Rẹ̀ àwọn ènìyàn búburú sílẹ̀.

7. Fi ọpẹ́ kọrin sí Olúwafi ohun èlò orin olókùn yin Ọlọ́run.

8. Ó fi ìkuukù bo àwọ sánmọ̀ó rọ òjò sí orílẹ̀ ayéó mú kí koríko hù lórí àwọn òkè

9. Ó pèṣè oúnjẹ fún àwọn ẹrankoàti fún awọn ọmọ àdàbà ní ìgbà tí wọ́n bá ń ké.

10. Òun kò ní inú dídùn nínú agbára ẹsinbẹ́ẹ̀ ni Òun kò ní ayọ̀ sí ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin

11. Olúwa ní ayọ̀ nínú àwọn tí ó bẹ̀rù Rẹ̀,sí àwọn tí ó ní ìrètí nínú àánú Rẹ̀.

12. Yin Olúwa, ìwọ Jérúsálẹ́mùyin Ọlọ́run Rẹ̀, ìwọ Síónì.

13. Nítorí tí ó ti mú ọ̀pá ìdábùú ìbodè Rẹ̀ lágbára;Òun sì ti bùkún fún àwọn ọmọ Rẹ̀ nínú Rẹ

14. Òun jẹ́ kí àlàáfíà wà ní àwọn ẹnu ibodè Rẹ̀òun sì fi jéró dáradára tẹ́ ọ lọ́rùn.

15. Òun sì rán àṣẹ Rẹ̀ sí ayéọ̀rọ̀ Rẹ̀ sáré tete.

16. Ó fi sino fún ni bi irun àgùntànó sì fọ́n ìrì idídì ká bí eérú

17. Ó rọ òjò yìnyín Rẹ̀ bí òkúta wẹ́wẹ́ta ni ó lè dúró níwájú òtútù Rẹ̀

18. Ó rán ọ̀rọ̀ Rẹ̀ jáde ó sì mú wọn yọ̀ó mú kí afẹ́fẹ́ Rẹ̀ fẹ́ó sì mú odò Rẹ̀ sàn.

19. Ó sọ ọ̀rọ̀ Rẹ̀ di mímọ̀ fún Jákọ́bùàwọn òfin àti ìlànà Rẹ̀ fún Ísírẹ́lì

20. Òun kó tí ṣe irú èyí sí orílẹ̀ èdè kan rí, Bí ó ṣe ti ìdájọ́ Rẹ̀wọn ko mọ òfin Rẹ̀.Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

Ka pipe ipin Sáàmù 147