Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 147:10-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Òun kò ní inú dídùn nínú agbára ẹsinbẹ́ẹ̀ ni Òun kò ní ayọ̀ sí ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin

11. Olúwa ní ayọ̀ nínú àwọn tí ó bẹ̀rù Rẹ̀,sí àwọn tí ó ní ìrètí nínú àánú Rẹ̀.

12. Yin Olúwa, ìwọ Jérúsálẹ́mùyin Ọlọ́run Rẹ̀, ìwọ Síónì.

13. Nítorí tí ó ti mú ọ̀pá ìdábùú ìbodè Rẹ̀ lágbára;Òun sì ti bùkún fún àwọn ọmọ Rẹ̀ nínú Rẹ

14. Òun jẹ́ kí àlàáfíà wà ní àwọn ẹnu ibodè Rẹ̀òun sì fi jéró dáradára tẹ́ ọ lọ́rùn.

15. Òun sì rán àṣẹ Rẹ̀ sí ayéọ̀rọ̀ Rẹ̀ sáré tete.

16. Ó fi sino fún ni bi irun àgùntànó sì fọ́n ìrì idídì ká bí eérú

17. Ó rọ òjò yìnyín Rẹ̀ bí òkúta wẹ́wẹ́ta ni ó lè dúró níwájú òtútù Rẹ̀

18. Ó rán ọ̀rọ̀ Rẹ̀ jáde ó sì mú wọn yọ̀ó mú kí afẹ́fẹ́ Rẹ̀ fẹ́ó sì mú odò Rẹ̀ sàn.

19. Ó sọ ọ̀rọ̀ Rẹ̀ di mímọ̀ fún Jákọ́bùàwọn òfin àti ìlànà Rẹ̀ fún Ísírẹ́lì

Ka pipe ipin Sáàmù 147