Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 146:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa,fi ìyìn fún Olúwa, ìwọ ọkàn mi

2. Èmi yóò yin Olúwa ní gbogbo ayé mièmi yóò kọrin ìyìn sí Ọlọ́run,níwọ̀n ìgbà tí mo bá wà láàyè.

3. Ẹ má ṣe ní ìgbẹkẹ̀lé nínú àwọn ọmọ aládé,àní, ọmọ ènìyàn,lọ́wọ́ ẹni tí kò sí ìrànlọ́wọ́.

4. Ẹ̀mí Rẹ jáde lọ, ó padà sí erùpẹ̀ Rẹ̀:Ní ọjọ́ náà gan, èrò wọn yóò di òfo:

5. Ìbùkún ni fún ẹni tíỌlọ́run Jákọ́bù ń ṣe ìrànlọ́wọ́ Rẹ̀tí ìrètí Rẹ̀ wà nínú Olúwa Ọlọ́run Rẹ̀,

6. Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayéòkun àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú wọn Olúwa, tí ó pa òtítọ́ mọ́ títí láéláé

Ka pipe ipin Sáàmù 146