Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 145:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Èmi yóò gbé ọ ga, Ọlọ́run ọba mi;Èmi yóò yin orúkọ Rẹ̀ láé àti láéláé

2. Ní ojoojúmọ́ èmi yóò yìn ọ́èmi yóò sì pòkìkí orúkọ Rẹ láé àti láéláé.

3. Títóbi ni Olúwa. Òun sì ni ó yẹ láti fi ìyìn fún púpọ̀púpọ̀:kò sí ẹni tí ó lè wọn títóbi Rẹ̀.

4. Ìran kan yóò máa yin iṣẹ́ Rẹ dé ìran mìíràn;wọn yóò máa sọ iṣẹ́ agbára Rẹ

5. Wọn yóò máa sọ ìyìn ọlá ńlá Rẹ tí ó lógo,èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú iṣẹ́ ìyanu Rẹ.

6. Wọn yóò sọ iṣẹ́ agbára Rẹ tí ó ní ẹ̀rùèmi yóò kéde iṣẹ́ ńlá Rẹ̀.

7. Wọn yóò ṣe ìrántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ìwà rere Rẹ àti orin ayọ̀ òdodo Rẹ.

Ka pipe ipin Sáàmù 145