Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 139:6-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Irú ìmọ̀ yìí ṣe ohun ìyanu fún mi jù;ó ga, èmi kò le mọ̀.

7. Níbo ní èmi yóò gbé lọ kúrò ní ọwọ́ ẹ̀mí Rẹ?Tàbí níbo ní èmi yóò sáré kúrò níwájú Rẹ?

8. Bí èmi bá gòkè lọ sí ọ̀run, ìwọ wà níbẹ̀;bí èmí ba sì tẹ́ ẹní mi ní ipò òkú,kíyèsí i, ìwọ wà níbẹ̀.

9. Èmi ìbá mú ìyẹ́ apá òwúrọ̀,kí èmi sì lọ jókòó ní ìhà òpin òkun;

10. Àní níbẹ̀ náà ni ọwọ́ Rẹ̀ yóò fà míọwọ́ ọ̀tún Rẹ yóò sì dì mí mú.

11. Bí mo bá wí pé, ǹjẹ́ kí òkùnkùn kí ó bò mí mọ́lẹ̀;kí ìmọ́lẹ̀ kí ó di òru yí mi ká.

12. Nítòótọ́ òkùnkùn kì í ṣú lọdọ̀ Rẹ;ṣùgbọ́n òru tan ìmọ́lẹ̀ bí ọ̀sán;àti òkùnkùn àti ọ̀sán, méjèèjìbákan náà ní fún ọ.

13. Nítorí ìwọ ní ó dá ọkàn mi;ìwọ ní ó bò mí mọ́lẹ̀ nínú ìyá mi.

14. Èmi yóò yìn ọ nítorí tẹ̀rùtẹ̀rù àtitìyanu tìyanu ní a dá mi;ìyanu ní isẹ́ Rẹ; èyí nì níọkàn mi sì mọ̀ dájúdájú

15. Ẹ̀dá ara mi kò pamọ́ kúrò lọdọ̀ Rẹ,nígbà tí á dá mi ní ìkọ̀kọ̀,tí a sì ń ṣiṣẹ́ ní àràbarà níìhà ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé.

16. Ojú Rẹ̀ ti rí ohun ara mi tí ó wà láìpé:àti nínú ìwé Rẹ ni a ti kọ gbogbo wọn sí,ní ojojumọ́ ni a ń dá wọn,nígbà tí ọ̀kan wọn kò tí i sí.

17. Ọlọ́run, ìrò inú Rẹ tí ṣe iyebíye tó fún mi,iye wọn ti pọ̀ tó!

Ka pipe ipin Sáàmù 139