Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 137:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ẹ̀bá odò Bábílónì, níbẹ̀ ní àwa gbé jókòóàwa sì sunkún nígbà tí àwa rántí Síónì.

2. Àwa fi dùùrù wa kọ́ sí orí igi wílóò,tí ó wà láàrin Rẹ̀.

3. Nítorí pé níbẹ̀ ní àwọntí ó kó wa ní ìgbékùn bèèrè orin lọ́wọ́ wá,àti àwọn tí ó ni wá lára bèèrè ìdárayá wí pé;ẹ kọ orin Síónì kan fún wa.

4. Àwa o ti ṣe kọ orin Olúwa ni ilẹ̀ àjèjì

5. Jérúsálẹ́mù, bí èmi bá gbàgbé Rẹjẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tún mi kí ó gbàgbé ìlò Rẹ.

6. Bí èmi kò bá rántí Rẹ,jẹ́ kí ahọ́n mi kí ó lẹ̀ mọ́ èrìgì mi;bí èmi kò bá fi Jérúsálẹ́mù ṣáájúolórí ayọ̀ mi gbogbo.

7. Olúwa rántí ọjọ́ Jérúsálẹ́mù,lára àwọn ọmọ Édómù,àwọn ẹni tí ń wí pé,wó o palẹ̀, wó o palẹ̀ de ìpílẹ̀ Rẹ̀!

8. Ìwọ, ọmọbìnrin Bábílónì, ẹni tí a o parun;ìbùkún ní fún ẹni tí ó san án fúnọ bí ìwọ ti rò sí wa.

9. Ìbùkún ní fún ẹni tí ó mú tí ó sì fiọmọ wẹ́wẹ́ Rẹ̀ ṣán òkúta.

Ka pipe ipin Sáàmù 137