Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 135:1-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ẹ yìn Olúwa, ẹ yìn orúkọ Olúwa;Ẹ yìn ín, ẹ̀yin ìránṣẹ́ Olúwa.

2. Ẹ̀yin tí ń dúró ní ilé Olúwa,nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run wa.

3. Ẹ yin Olúwa: nítorí tí Olúwa ṣeun;ẹ kọrin ìyìn sí orúkọ Rẹ̀; ní torí tí ó dùn.

4. Nítorí tí Olúwa ti yàn Jákọ́bù fún ara Rẹ̀;àní Ísírẹ́lì fún ìṣúra ààyò Rẹ̀.

5. Nítorí tí èmi mọ̀ pé Olúwa tóbi,àti pé Olúwa jù gbogbo òrìṣà lọ.

6. Ohunkóhun tí ó wu Olúwa, Òun ní iṣe ní ọ̀run,àti ní ayé, ní òkun àti ní ọ̀gbun gbogbo.

7. Ó mú ìkuku góke láti òpin ilẹ̀ wá:ó dá mọ̀nàmọ́ná fún òjo:ó ń mú afẹ́fé ti inú ilẹ̀ ìṣúra Rẹ̀ wá.

8. Ẹni tí ó kọlu àwọn àkọ́bí Éjíbítì,àti tí ènìyàn àti ti ẹranko.

9. Ẹni tí ó rán àmì àti iṣẹ ìyanu sí àrin Rẹ̀,ìwọ Éjíbítì, sí ara Fáráò,àti sí ara àwọn ìránṣẹ́ Rẹ̀ gbogbo.

10. Ẹni tí ó kọlu àwọn orílẹ̀ èdè púpọ̀,tí ó sì pa àwọn alágbára ọba.

11. Síónì, ọba àwọn ará Ámorì, àti Ógù,ọba Báṣánì, àti gbogbo ìjọba Kénánì:

12. Ó sì fi ilẹ̀ wọn fúnni ní ìní,ìní fún Ísírẹ́lì, ènìyàn Rẹ̀.

Ka pipe ipin Sáàmù 135