Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 132:1-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Olúwa, rántí Dáfídìnínú gbogbo ìpọ́njú Rẹ̀:

2. Ẹni tí ó ti búra fún Olúwa,tí ó sì ṣe ìlèrí fún Alágbára Jákọ́bù pé.

3. Nítòótọ́, èmi kì yóò wọ inú àgọ́ ilé mi lọ,bẹ́ẹ̀ èmi kì yóò gùn orí àkéte mi:

4. Èmi kì yóò fi oorun fún ojú mi,tàbí òògbé fún ìpéǹpéjú mi,

5. Títí èmi ó fi rí ibi fún Olúwa,ibùjókòó fún Alágbára Jákọ́bù.

6. Kíyèsí i, àwa gbúroo Rẹ̀ ni Éfúrátà:àwa rí i nínú oko ẹgàn náà.

7. Àwa ó lọ sínú àgọ́ Rẹ̀:àwa ó máa sìn níbi àpótí-ìtìsẹ̀ Rẹ̀

8. Olúwa, dìde sí ibi ìsinmi Rẹ:ìwọ, àti àpótí agbára Rẹ.

9. Kí a fi òdodo wọ àwọn àlùfáà Rẹ:kí àwọn ènìyàn mímọ́ Rẹ kí ó máa hó fún ayọ̀.

10. Nítorí tí Dáfídì ìránṣẹ́ Rẹ̀Má ṣe yí ojú ẹni-òróró Rẹ padà.

Ka pipe ipin Sáàmù 132