Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 121:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Èmi yóò gbé ojú mi sórí òkè wọ̀n-ọn-nì—níbo ni ìrànlọ́wọ́ mi yóò ti wá

2. Ìrànlọ́wọ́ mi tí ọwọ́ Olúwa wáẸni tí ó dá ọ̀run òun ayé

3. Òun kì yóò jẹ́ kí ẹṣẹ̀ Rẹ̀ kí ó yẹ̀;ẹni tí ó pa ọ́ mọ́ kì í tòògbé.

4. Kíyèsí, ẹni tí ń pa Ísírẹ́lì mọ́,kì í tòògbé bẹ́ẹ̀ ni kì í sùn.

5. Olúwa ni olùpamọ́ Rẹ; Olúwa ní òjìji Rẹ ní ọwọ́ ọ̀tún Rẹ

6. Oòrùn kì yóò pa ọ ní ìgbà ọ̀sántàbí òṣùpá ní ìgbà òru.

7. Olúwa yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú ibi gbogboyóò pa ọkàn Rẹ mọ́

8. Olúwa yóò pa àlọ àti ààbọ̀ Rẹ mọ́láti ìgbà yìí lọ àti títí láéláé.

Ka pipe ipin Sáàmù 121