Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 119:93-109 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

93. Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ Rẹ láé,nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́

94. Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹèmi ti wá ẹ̀kọ́ Rẹ.

95. Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run,ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsí ẹ̀rí Rẹ.

96. Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin;ṣùgbọ́n àṣẹ Rẹ aláìlópin ni.

97. Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin Rẹ tó!Èmi ń ṣe àṣàrò nínú Rẹ̀ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.

98. Àṣẹ Rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀ta mi lọ,nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.

99. Èmi ní iyè ińu ju gbogbo olùkọ́ mi lọ,nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin Rẹ.

100. Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ,nítorí mo gba ẹ̀kọ́ Rẹ.

101. Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibinítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ Rẹ.

102. Èmi kò yà kúrò nínú òfin Rẹ,nítorí ìwọ fún rarẹ̀ ni ó kọ́ mi.

103. Báwo ni ọ̀rọ̀ Rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó,ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!

104. Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ Rẹ;nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.

105. Ọ̀rọ̀ Rẹ ni ó ṣe fítílà sí ẹṣẹ̀ miàti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi

106. Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọnwí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo Rẹ.

107. A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ Rẹ

108. Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi,kí o sì kọ́ mi ní òfin Rẹ̀.

109. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ minígbà gbogbo,èmi kò ní gbàgbé òfin Rẹ.

Ka pipe ipin Sáàmù 119