Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 119:85-99 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

85. Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi,tí ó lòdì sí òfin Rẹ.

86. Gbogbo àsẹ Rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé:rànmílọ́wọ́, nítorí ènìyànń ṣe inúnibíni sí mi láì nídìí.

87. Wọ́n fẹ́rẹ̀ẹ́ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé,ṣùgbọ́n èmi kò kọ̀ ẹ̀kọ́ Rẹ.

88. Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ Rẹ,èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu Rẹ̀ gbọ́.

89. Ọ̀rọ̀ Rẹ, Olúwa, títí láé ni;ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run

90. Òtítọ́ Rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran;ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.

91. Òfin Rẹ dúró di ònínítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.

92. Bí òfin Rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi,èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.

93. Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ Rẹ láé,nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́

94. Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹèmi ti wá ẹ̀kọ́ Rẹ.

95. Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run,ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsí ẹ̀rí Rẹ.

96. Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin;ṣùgbọ́n àṣẹ Rẹ aláìlópin ni.

97. Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin Rẹ tó!Èmi ń ṣe àṣàrò nínú Rẹ̀ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.

98. Àṣẹ Rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀ta mi lọ,nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.

99. Èmi ní iyè ińu ju gbogbo olùkọ́ mi lọ,nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin Rẹ.

Ka pipe ipin Sáàmù 119