Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 119:80-89 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

80. Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin Rẹ,kí ojú kí ó má ṣe tì mí.

81. Ọkàn mi ń fojú sọ́nà nítorí ìgbàlà Rẹ,ṣùgbọ́n èmi tí mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ Rẹ.

82. Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wí wo ìpinu Rẹ;èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”

83. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí àmọ́ wáìnì nínú èéfín,èmi kò gbàgbé òfin Rẹ.

84. Báwo ni ìránṣẹ́ Rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó?Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọntí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?

85. Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi,tí ó lòdì sí òfin Rẹ.

86. Gbogbo àsẹ Rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé:rànmílọ́wọ́, nítorí ènìyànń ṣe inúnibíni sí mi láì nídìí.

87. Wọ́n fẹ́rẹ̀ẹ́ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé,ṣùgbọ́n èmi kò kọ̀ ẹ̀kọ́ Rẹ.

88. Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ Rẹ,èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu Rẹ̀ gbọ́.

89. Ọ̀rọ̀ Rẹ, Olúwa, títí láé ni;ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run

Ka pipe ipin Sáàmù 119