Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 119:58-74 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

58. Èmi ti wá ojú Rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi:fún mi ní oore ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu Rẹ.

59. Èmi ti kíyèsí ọ̀nà mièmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin Rẹ.

60. Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́raláti gbọ́ràn sí àṣẹ Rẹ.

61. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn,èmi kò ní gbàgbé òfin Rẹ.

62. Ní àárin ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọnítorí òfin òdodo Rẹ̀.

63. Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù Rẹ,sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ Rẹ̀.

64. Ayé kún fún ìfẹ́ Rẹ OlúwaKọ́ mi ní òfin Rẹ.

65. Ṣe rere sí ìránṣẹ́ Rẹgẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Rẹ, Olúwa.

66. Kọ́ mi ni ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere,nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ Rẹ.

67. Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti sìnà,ṣùgbọ́n ni ìsinsinyí èmi gbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ Rẹ̀.

68. Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni;kọ́ mi ní ìlànà Rẹ.

69. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti Rẹ̀ mí pẹ̀lú èkéèmi pa ẹ̀kọ́ Rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.

70. Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú,ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin Rẹ.

71. Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójúnítorí kí èmi lè kọ́ òfin Rẹ.

72. Òfin tí ó jáde láti ẹnu Rẹ ju iyebíye sí mi lọó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ

73. Ọwọ́ Rẹ ní ó dá mi tí ó sì mọ mí;fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ Rẹ.

74. Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù Rẹ máa yọ̀nígbà tí wọ́n bá rí mi,nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ Rẹ.

Ka pipe ipin Sáàmù 119