Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 119:48-63 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

48. Èmi gbé ọwọ̀ mi sókè nítorí àṣẹ Rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn,èmi sì ń ṣe àsàrò òfin Rẹ̀.

49. Rántí ọ̀rọ̀ Rẹ̀ sí ìránṣẹ́ Rẹ,nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.

50. Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí:ìpinu Rẹ pa ayé mi mọ́.

51. Àwọn agbéraga fi mi ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró,ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin Rẹ.

52. Èmi rántí àwọn òfin Rẹ ìgbàanì, Olúwa,èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.

53. Ìbínú dìmí mú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburútí wọ́n ti kọ òfin Rẹ sílẹ̀.

54. Òfin Rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin miníbikíbi tí èmi ń gbé.

55. Ní òru èmi rántí orúkọ Rẹ, Olúwa,èmi yóò sì pa òfin Rẹ mọ́

56. nitori ti mogba ẹ̀kọ́ Rẹ gbọ́.

57. Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa:èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ Rẹ.

58. Èmi ti wá ojú Rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi:fún mi ní oore ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu Rẹ.

59. Èmi ti kíyèsí ọ̀nà mièmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin Rẹ.

60. Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́raláti gbọ́ràn sí àṣẹ Rẹ.

61. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn,èmi kò ní gbàgbé òfin Rẹ.

62. Ní àárin ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọnítorí òfin òdodo Rẹ̀.

63. Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù Rẹ,sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ Rẹ̀.

Ka pipe ipin Sáàmù 119