Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 119:3-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Wọn kò ṣe ohun tí kò dára;wọ́n rìn ní ọ̀nà Rẹ̀.

4. Ìwọ ti la ìlànà Rẹ̀ sílẹ̀kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.

5. Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣinláti máa pa òfin Rẹ̀ mọ́!

6. Nígbà náà, ojú kò ní tì mínígbà tí mo bá ń kíyèsí àṣẹ Rẹ̀ gbogbo.

7. Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣinbí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo Rẹ̀.

8. Èmi yóò gbọ́ràn sí asẹ Rẹ̀:Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátapáta.

9. Báwo ni àwọn èwe ènìyàn yóò ti ṣe pa ọ̀nà Rẹ̀ mọ́?Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ Rẹ.

10. Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mimá ṣe jẹ́ kí èmi yàpa kúrò nínú àṣẹ̀ Rẹ.

11. Èmi ti pa ọ̀rọ̀ Rẹ mọ́ ní ọkàn mikí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ

12. Ìyìn ni fún Olúwa;kọ́ mi ní àsẹ Rẹ.

13. Pẹ̀lú ètè mi èmi tún sírògbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu Rẹ.

14. Èmi yọ̀ nínú títẹ̀lé òrin Rẹbí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọlá ńlá.

Ka pipe ipin Sáàmù 119