Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 119:29-48 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tànfún mi ní oore ọ̀fẹ́ nípa òfin Rẹ.

30. Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin Rẹ.

31. Èmi yára di òfin Rẹ mú. Olúwamá ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.

32. Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ Rẹ,nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.

33. kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ Rẹ;nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.

34. Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin Rẹ mọ́èmi yóò sì máa kíyèsíi pẹ̀lú ọkàn mi.

35. Fi ipa ọ̀nà àṣẹ Rẹ hàn mí,nítorí nínú Rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.

36. Yí ọkàn mi padà sí òfin Rẹ̀kí ó má ṣe sí ojú kòkòrò mọ́.

37. Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán:pa ayé mí mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Rẹ.

38. Mú ìlérí Rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ Rẹ,nítorí òfin Rẹ dára.

39. Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rùni torí tí idájọ́ Rẹ dára.

40. Kíyèsíi ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ Rẹ!Pa ayé mí mọ́ nínú òdodo Rẹ.

41. Jẹ́ kí ìfẹ́ Rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa,ìgbàlà Rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu Rẹ;

42. Nígbà náà ni èmi yóò dáẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn,nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ Rẹ.

43. Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu minítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ Rẹ

44. Èmi yóò máa gbọ́ràn sí òfin Rẹ nígbà gbogboláé àti láéláé.

45. Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira,nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ Rẹ̀ jáde.

46. Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin Rẹ níwájú àwọn ọbaojú kì yóò sì tì mí,

47. Nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ Rẹnítórí èmi ni ìfẹ́ wọn.

48. Èmi gbé ọwọ̀ mi sókè nítorí àṣẹ Rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn,èmi sì ń ṣe àsàrò òfin Rẹ̀.

Ka pipe ipin Sáàmù 119