Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 119:105-120 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

105. Ọ̀rọ̀ Rẹ ni ó ṣe fítílà sí ẹṣẹ̀ miàti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi

106. Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọnwí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo Rẹ.

107. A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ Rẹ

108. Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi,kí o sì kọ́ mi ní òfin Rẹ̀.

109. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ minígbà gbogbo,èmi kò ní gbàgbé òfin Rẹ.

110. Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi,ṣùgbọ́n èmi kò sìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ Rẹ.

111. Òfin Rẹ ni ogún mi láéláé;àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.

112. Ọkàn mi ti lé pípa òfin Rẹ mọ́láé dé òpin.

113. Èmi kóríra àwọn ọlọ́kàn méjì,ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin Rẹ.

114. Ìwọ ni ààbò mi àti aṣà mi;èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ Rẹ.

115. Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú,kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!

116. Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Rẹ,kí èmi kí ó lè yèMá sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.

117. Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu;nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin Rẹ.

118. Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó sìnà kúrò nínú òfin Rẹ,nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.

119. Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọyọ kúrò bí i ìdàrọ́;nítorí náà, èmi fẹ́ òfin ẹ̀.

120. Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí Rẹ̀:èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin Rẹ

Ka pipe ipin Sáàmù 119