Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 119:100-107 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

100. Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ,nítorí mo gba ẹ̀kọ́ Rẹ.

101. Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibinítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ Rẹ.

102. Èmi kò yà kúrò nínú òfin Rẹ,nítorí ìwọ fún rarẹ̀ ni ó kọ́ mi.

103. Báwo ni ọ̀rọ̀ Rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó,ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!

104. Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ Rẹ;nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.

105. Ọ̀rọ̀ Rẹ ni ó ṣe fítílà sí ẹṣẹ̀ miàti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi

106. Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọnwí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo Rẹ.

107. A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ Rẹ

Ka pipe ipin Sáàmù 119