Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 118:7-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Olúwa n bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ miNítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìfẹ́ mi lórí àwọn ti ó kórìíra mi.

8. Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwaju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.

9. Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwaju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ aládé lọ.

10. Gbogbo àwọn orílẹ̀ èdè yí mi káàkiri,ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò

11. Wọn yí mi ká kiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́,ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù

12. Wọn gbá yìnìn yí mí ká bí oyin,ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún;ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.

13. Ìwọ tì mi gidigidi kí ń lè subú,ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.

14. Olúwa ni agbára àti orin mi;ó si di ìgbàlà mi.

15. Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo:“ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!

16. Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbé ga;ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”

Ka pipe ipin Sáàmù 118