Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 118:21-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dámi lóhùn;ìwọ sì di ìgbàlà mi.

22. Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀ sílẹ̀ni ó di pàtàkì òkúta igun ilé;

23. Olúwa ti ṣe èyíó ṣe ìyanu ní ojú wa.

24. Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá:ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú Rẹ̀.

25. Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.

26. Ìbùkún ni fún àwọn tí ó wá ní orúkọ Olúwa.Láti ilé Olúwa wá ní àwa fi ìbùkún fún ọ.

27. Olúwa ni Ọlọ́run,ó ti mú ìmọ́lẹ̀ Rẹ̀ tàn sí wa lárapẹ̀lú ẹká igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ

28. Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ;ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga

Ka pipe ipin Sáàmù 118