Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 118:19-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu ọ̀nà òdodo fún mi:èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.

20. Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwaibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.

21. Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dámi lóhùn;ìwọ sì di ìgbàlà mi.

22. Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀ sílẹ̀ni ó di pàtàkì òkúta igun ilé;

23. Olúwa ti ṣe èyíó ṣe ìyanu ní ojú wa.

24. Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá:ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú Rẹ̀.

25. Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.

26. Ìbùkún ni fún àwọn tí ó wá ní orúkọ Olúwa.Láti ilé Olúwa wá ní àwa fi ìbùkún fún ọ.

Ka pipe ipin Sáàmù 118