Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 106:42-48 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

42. Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọ́n lójúwọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.

43. Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n,Ṣíbẹ̀ wọ́n si ń ṣọ̀tẹ̀ sí ìwọ́n sì sòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

44. Ṣùgbọ́n o kíyèsí wọn nítorí ìṣòronígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn;

45. Ó rántí májẹ̀mú Rẹ̀ nítorí wọnNítorí agbára ìfẹ́ Rẹ̀, ó ṣàánú wọn.

46. Lójú gbogbo àwọn tí o kó wọn ní ìgbèkùnó mú wọn rí àánú.

47. Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa,kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrin àwọn aláìkọlàláti máa fí ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ Rẹláti máa ṣògo nínú ìyìn Rẹ.

48. Olùbùkún ni Olúwa,Ọlọ́run Ísírẹ́lì, láti ìrandíranJẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!”Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!

Ka pipe ipin Sáàmù 106