Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 106:39-46 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

39. Wọn si fi ìṣe ara wọn sọ arawọn di aláìmọ́, wọ́n sì ṣepanṣágà lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.

40. Nígbà náà Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn Rẹ̀ó sì kórìíra àwọn ènìyàn Rẹ̀

41. Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀ èdè lọ́wọ́,àwọn ọ̀tá wọn sì jọba lórí wọn.

42. Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọ́n lójúwọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.

43. Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n,Ṣíbẹ̀ wọ́n si ń ṣọ̀tẹ̀ sí ìwọ́n sì sòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

44. Ṣùgbọ́n o kíyèsí wọn nítorí ìṣòronígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn;

45. Ó rántí májẹ̀mú Rẹ̀ nítorí wọnNítorí agbára ìfẹ́ Rẹ̀, ó ṣàánú wọn.

46. Lójú gbogbo àwọn tí o kó wọn ní ìgbèkùnó mú wọn rí àánú.

Ka pipe ipin Sáàmù 106