Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 106:33-41 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

33. Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí ẹ̀mí Ọlọ́run.Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mósè wá.

34. Wọn kò pa àwọn ènìyàn rungẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí sọ fún wọn,

35. Ṣùgbọ́n wọn dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀ èdè,wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn

36. Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọntí o di ìkẹ́kùn fún wọn.

37. Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rúbọàti àwọn ọmọbìnrin fún òrìsà.

38. Wọn ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀.Ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọnọmọbìnrin wọn.Wọn fi wọ́n rúbọ sí ère Kénánì, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀

39. Wọn si fi ìṣe ara wọn sọ arawọn di aláìmọ́, wọ́n sì ṣepanṣágà lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.

40. Nígbà náà Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn Rẹ̀ó sì kórìíra àwọn ènìyàn Rẹ̀

41. Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀ èdè lọ́wọ́,àwọn ọ̀tá wọn sì jọba lórí wọn.

Ka pipe ipin Sáàmù 106