Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 106:22-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

22. Iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Ámùàti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá òkun pupa

23. Bẹ́ẹ̀ ní, ó sọ wí pé oun yóò pa wọ́n runbí kò ba ṣe tí Mósè, tí ó yàn,tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náàtí ó pa ìbínú Rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́

24. Nígbà náà, wọn kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náàwọn kò gba ilérí Rẹ̀ gbọ́.

25. Wọn ń kùn nínú àgọ́ wọnwọn kò sì gbọ́ràn sí Olúwa.

26. Bẹ́ẹ̀ ni ó gbé ọwọ́ Rẹ̀ sókè sí wọnkí òun le jẹ́ kí wọn ṣubú nínú ihà,

27. Láti jẹ́ kí àwọn ọmọ Rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀ èdèláti fọ́nu wọn káàkiri lórí ilẹ̀.

28. Wọn dá ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Péórù,wọn sì ń jẹ ẹbọ ti a rú sí àwọn òkú òrìṣà

Ka pipe ipin Sáàmù 106