Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 106:15-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n bèèrè fúnṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.

16. Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mósèpẹ̀lú Árónì, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.

17. Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Dátanì mìó bo ẹgbẹ́ Àbìrámù mọ́lẹ̀

18. Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ ẹ̀yin Rẹ̀;iná jo àwọn ènìyàn búburú.

19. Ní Hórébù wọ́n ṣe ẹ̀gbọ̀rọ̀ màlúùwọn sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara ìrìn.

20. Wọn pa ògo wọn dàsí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.

21. Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí í gbàwọ́nẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá fún Éjíbítì,

22. Iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Ámùàti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá òkun pupa

23. Bẹ́ẹ̀ ní, ó sọ wí pé oun yóò pa wọ́n runbí kò ba ṣe tí Mósè, tí ó yàn,tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náàtí ó pa ìbínú Rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́

24. Nígbà náà, wọn kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náàwọn kò gba ilérí Rẹ̀ gbọ́.

25. Wọn ń kùn nínú àgọ́ wọnwọn kò sì gbọ́ràn sí Olúwa.

26. Bẹ́ẹ̀ ni ó gbé ọwọ́ Rẹ̀ sókè sí wọnkí òun le jẹ́ kí wọn ṣubú nínú ihà,

27. Láti jẹ́ kí àwọn ọmọ Rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀ èdèláti fọ́nu wọn káàkiri lórí ilẹ̀.

28. Wọn dá ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Péórù,wọn sì ń jẹ ẹbọ ti a rú sí àwọn òkú òrìṣà

29. Wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣeàjàkálẹ̀-àrùn jáde láàrin wọn.

30. Ṣùgbọ́n Fínéhásì dìde láti dá sí i,àjàkálẹ̀-àrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán

31. A sì ka èyí sí òdodo fún un àtifún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀

Ka pipe ipin Sáàmù 106