Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 106:10-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọnláti ọwọ́ ọ̀tá ni ó ti gbà wọ́n

11. Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn, bẹ́ẹ̀ nikò sí èyí tí ó yè nínú wọn.

12. Nígbà náà wọn gba ìpínnú Rẹ gbọ́wọ́n sì kọrin ìyìn Rẹ.

13. Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣewọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn Rẹ

14. Nínú ihà ni wọn tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́nínú aṣálẹ̀ wọn dán Ọlọ́run wò

15. Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n bèèrè fúnṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.

16. Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mósèpẹ̀lú Árónì, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.

17. Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Dátanì mìó bo ẹgbẹ́ Àbìrámù mọ́lẹ̀

18. Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ ẹ̀yin Rẹ̀;iná jo àwọn ènìyàn búburú.

19. Ní Hórébù wọ́n ṣe ẹ̀gbọ̀rọ̀ màlúùwọn sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara ìrìn.

20. Wọn pa ògo wọn dàsí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.

21. Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí í gbàwọ́nẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá fún Éjíbítì,

22. Iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Ámùàti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá òkun pupa

23. Bẹ́ẹ̀ ní, ó sọ wí pé oun yóò pa wọ́n runbí kò ba ṣe tí Mósè, tí ó yàn,tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náàtí ó pa ìbínú Rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́

24. Nígbà náà, wọn kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náàwọn kò gba ilérí Rẹ̀ gbọ́.

Ka pipe ipin Sáàmù 106